< Lucas 13 >

1 Y andré ocona matejo chiros sinaban oté yeques, sos le penaban nuevas es Galileyes, cuya rati habia bucharado Pilato andré la es sacrificios de junos.
Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
2 Y Jesus les rudeló, penando: ¿Penchabelais, que ocolas Galileyes sináron chorés butér que sares os averes, por terelar padecido buchias oconas?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
3 Sangue penelo, que nanai: Tami si na querelareis penitencia, os sares merareis andré a mateja beda.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
4 Andiar sasta tambien ocolas deque y otor manuces, opré coines peró o quer baro andré Siloé, y los maró: ¿penchabelais, que junos debisáron butér qus os sares manuces sos socabelaban andré Jerusalém?
Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
5 Sangue penelo, que nanai: tami si na querelareis penitencia, os sares merareis andré a mateja beda.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
6 Y penelaba tambien ocona parabola: Manu terelaba carschta chabéra chitalada andré sun resis, y chaló á orotar mibao andré siró, y na le alachó.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
7 Y penó al paillo sos randiñó a resis: Diquela; trin berjis sinela que abillelo a orotar mibao andré ocona carschta chabera, y na lo alachó: velala pues: ¿para qué terela de ucharar aun a chiquen?
Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
8 Tami ocola rudeló y le penó: Erañó: mequelela aun ocona berji, y la cavaré al crugos, y le chibaré groñi:
“Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
9 Astis sat ocono diñare mibao: y si nanai, la velarás despues.
Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
10 Y sinaba bedando andré a Synagoga de junos as Canchés.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
11 Y he acoi yeque cadchi, sos terelaba bengui de merdipen deque y otor berjis habia: y sinaba encorbada que na le astis dicar acia opré.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
12 Pur la dicó Jesus, la araqueró á siró, y la penó: Cadchi, libre sinelas de tun merdipén.
Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
13 Y chibó opré siró as bastes, y yescotria se ardiñó, y diñaba chimusolano á Debél.
Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
14 Y ustilando a varda o Manclay e Synagoga, ululé presas Jesus habia chibado lacho andré la Canché, penó á la sueti: Zoi chibeses terelais, andré que astis randiñar: andré oconas pues abillad, y que chibele sangue lacho, y andré la Canché nanai.
Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
15 Y rudelando o Erañó penó: Sungales, saro yeque de sangue na despandela andré la Canché desquero goruy, ó desquero gel del olibal y lo lliguerela á piyar.
Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
16 ¿Y ocona chai de Abraham, á coin terelaba pandisarado Satanás deque y otor berjis, na sinela mistos despandarla de ocona trajata andré chibes de Canché?
Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
17 Y penando oconas buchias se pachibelaban sares os daschmanuces de ó: tami se alendaba sari a sueti de sarias as buchias, que ó querelaba chimusolanamente.
Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
18 Penelaba pues: ¿A qué buchi sinela semejante o chim de Debél, y á que buchi lo compararé?
Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
19 Semejante sinela al grano e mostaza, sos lo ustiló yeque manu y lo chitó andré desquero vea, y se queró baro, y se queró carschta udschi; y as ujarres e charos sobeláron opré desqueres senques.
Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
20 Y penó aver chiros: A qué penelaré, que o chim de Debél sinela semejante?
Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
21 Semejante sinela á la levadura, sos ustiló yeque cadchi, y la chibó andré trin melales de roi, disde que o saro se querase fermentado.
Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
22 Y chalaba por foros y gau, bedando y querelando drun ácia Jerusalém.
Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
23 Y le penó yeque manu: ¿Eraño, sinelan frimes junos sos se salvan? Y ó les penó:
Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
24 Querelad ezor á sicobaros andré por a bundal chinori: presas sangue penelo, que baribustres camelarán chalar andré, y na les astis.
“Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
25 Y pur o batu e quer terelare chalado andré, y pandado a bundal, sangue sinareis abrí, y os chitareis á araquerar á la bundal, penando: Erañó, pendrabanos: y ó os rudelará, penando: Na chanelo duque sinelais sangue:
Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
26 Entonces os chibareis á penar: Anglal de tucue jamemos y piyemos, y andré amares masqueres bedaste.
“Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
27 Y os penará: Na chanelo duque sangue sinelais: Chalaos de mangue sares os curadores e choripen.
“Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
28 Oté sinará o orabar, y o nacicar de danias, pur dicareis á Abraham, y á Isaac, y á Jacob, y á sares os Prophetas andré o chim de Debél, y sangue sinelais bucharados abrí.
“Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
29 Y abillarán de Boctaro, y de Occidente, y de Aquilón, y de Austro, y se bestelarán á la mensalle andré o chim de Debél.
Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
30 Y he acoi que sinelan segritones, junos sos sinarán brotobores, y que brotobores, junos sos sinarán segritones.
Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
31 Ocona matejo chibes se bigoreáron á ó yeques Phariseyes, y le penáron: Sicobelatucue de acoi, y chatucue, presas Herodes te camela marar.
Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
32 Y les penó: Chalad, y penad á ocola rubasuncha, que menda bucharelo bengues, y chibelo lacho achibes y tasáta, y al trincho chibes sinelo chichi.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
33 Tami jomte, que menda pirele achibes, y tasáta, y aver chibes: Presas n’astis que yeque Propheta merele abrí de Jerusalém.
Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
34 Jerusalém, Jerusalém, sos marelas á os Prophetas, y bucharélas barias á junos sos sinelan bichabados á tucue, ¿quantas begais camelé catanar tires chabores, sasta a cañi desqueres chiricles ostely desquerias alas, y na camelaste.
“Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
35 He acoi que á tucue sinará mequelada bi sueti tiro quer. Y á tucue penelo que na diquelarás mangue butér, disde que abilleli o chiros, pur penelais: Majarificable sinele ó sos abillele andré o nao e Erañoró.
Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”

< Lucas 13 >