< Psalmet 116 >

1 Unë e dua Zotin, sepse ai dëgjoi zërin tim dhe lutjet e mia.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Duke qenë se e ka kthyer ndaj meje veshin e tij, unë do ta kërkoj në gjithë ditët e jetës sime.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Vargonjtë e vdekjes më kishin rrethuar dhe ankthet e Sheolit më kishin pushtuar; fatkeqësia dhe dhembja më kishin vënë përfund. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 Atëherë i kërkova ndihmë Zotit: “O Zot, të lutem, më shpëto”.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 Zoti është i dhemshur dhe i drejtë, Perëndia ynë është i mëshirshëm.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 Zoti mbron njerëzit e thjeshtë; unë isha katandisur në një gjendje të mjeruar, dhe ai më shpëtoi.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Kthehu, o shpirti im, në prehjen tënde, sepse Zoti të mbushi me të mira.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Po, sepse ti ke çliruar jetën time nga vdekja, sytë e mi dhe lotët dhe këmbët e mia nga rrëzimi.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Unë do të eci në prani të Zotit në tokën e të gjallëve.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 Unë kam besuar dhe prandaj flas. Unë isha shumë i pikëlluar,
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 dhe thoja gjatë përhumbjes sime: “Çdo njeri është gënjeshtar”.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Ç’do t’i jap Zotit në këmbim të të gjitha të mirave që më ka bërë?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 Unë do të ngre kupën e shpëtimit dhe do të thërres emrin e Zotit.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Do të plotësoj zotimet e mia ndaj Zotit në prani të të gjithë popullit të tij.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Éshtë e çmueshme në sytë e Zotit vdekja e të shenjtëve të tij.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Unë jam me të vërtetë shërbëtori yt, o Zot, jam shërbëtori yt, bir i shërbëtores sate; ti i këpute lidhjet e mia.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Unë do të të ofroj një flijim falenderimi dhe do të përmend emrin e Zotit.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Do t’i plotësoj zotimet e mia Zotit në prani të të gjithë popullit të tij,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 në oborret e shtëpisë së Zotit, në mesin tënd, o Jeruzalem. Aleluja.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalmet 116 >