< Vajtimet 3 >

1 Unë jam njeriu që pa hidhërimin nën thuprën e tërbimit të tij.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Ai më ka udhëhequr dhe më ka bërë të eci nëpër terr dhe jo në dritë.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Po, kundër meje ai ka kthyer disa herë dorën e tij tërë ditën.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Ai ka konsumuar mishin tim dhe lëkurën time, ka coptuar kockat e mia.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Ka ndërtuar fortesa kundër meje, më ka rrethuar me hidhërim dhe me ankth.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Ka bërë që unë të banoj në vende plot errësirë, ashtu si të vdekurit prej shumë kohe.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Më ka ndërtuar një mur rreth e qark, me qëllim që unë të mos dal; e ka bërë të rëndë zinxhirin tim.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Edhe kur bërtas dhe kërkoj ndihmë me zë të lartë, ai nuk pranon të dëgjojë lutjen time.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Ai i ka mbyllur rrugët e mia me gurë të prerë, i ka bërë shtigjet e mia plot me prita.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Ai ka qenë për mua si një ari në pritë, si një luan në vende të fshehta.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Ka devijuar rrugët e mia, më ka coptuar dhe më ka dëshpëruar.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Ka nderur harkun e tij dhe më ka bërë objekt të shigjetave të tij.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Ka bërë të depërtojnë në zemrën time shigjetat e kukurës së tij.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Jam bërë tallja e tërë popullit tim, kënga e tij e tërë ditës.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Më ka ngopur me hidhërim, më ka bërë të pij pelin.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Më ka coptuar dhëmbët me zall, më ka mbuluar me hi.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Ke larguar shpirtin tim nga paqja, kam harruar mirëqënien.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Kam thënë: “Éshtë zhdukur besimi im dhe shpresa ime tek Zoti”.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Kujtohu për pikëllimin dhe për endjen time, për pelinin dhe hidhërimin.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Shpirti im kujtohet gjithnjë për këtë dhe është i rrëzuar brenda meje.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Këtë dua ta sjell në mëndje dhe prandaj dua të shpresoj.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Éshtë një hir i Zotit që nuk jemi shkatërruar plotësisht, sepse mëshirat e tij nuk janë mbaruar plotësisht.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Përtëriten çdo mëngjes; e madhe është besnikeria jote.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 “Zoti është pjesa ime”, thotë shpirti im, “prandaj do të kem shpresë tek ai.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Zoti është i mirë me ata që kanë shpresë tek ai, me shpirtin që e kërkon.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Gjë e mirë është të presësh në heshtje shpëtimin e Zotit.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Gjë e mirë është për njeriun të mbajë zgjedhën në rininë e tij.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Le të ulet i vetmuar dhe të qëndrojë në heshtje kur Perëndia ia imponon.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Le ta vërë gojën e tij në pluhur, ndofta ka ende shpresë.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Le ti japë faqen atij që e godet, të ngopet me fyerje.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Sepse Zoti nuk hedh poshtë për gjithnjë;
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 por, në rast se të hidhëron, do ti vijë keq sipas shumicës së zemërmirësive të tij,
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 sepse nuk e bën me kënaqësi poshtërimin dhe hidhërimin e bijve të njerëzve.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Kur dikush shtyp nën këmbët e tij tërë robërit e dheut,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 kur dikush shtrëmbëron të drejtën e një njeriu në prani të Më të Lartit,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 kur dikujt i bëhet një padrejtësi në çështjen e tij, a nuk e shikon Zoti?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Vallë kush thotë diçka që më pas realizohet, në rast se Zoti nuk e ka urdhëruar?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 E keqja dhe e mira a nuk vijnë vallë nga goja e Më të Lartit?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Pse vallë ankohet një njeri i gjallë, një njeri për ndëshkimin e mëkateve të tij?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Le të shqyrtojmë rrugët tona, t’i hetojmë dhe të kthehemi tek Zoti.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Le të ngremë lart zemrat tona dhe duart tona në drejtim të Perëndisë të qiejve.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Ne kemi kryer mëkate, kemi qënë rebelë dhe ti nuk na ke falur.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Je mbështjellë në zëmërimin tënd dhe na ke ndjekur, na ke vrarë pa mëshirë.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Ti je mbështjellë në një re, në mënyrë që asnjë lutje të mos kalonte dot.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Na ke bërë plehra dhe mbeturina në mes të popujve.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Tërë armiqtë tanë kanë hapur gojën kundër nesh.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Na ka rënë mbi trup tmerri, laku, dëshpërimi i thellë dhe shkatërrimi.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Rrëke uji rrjedhin nga sytë e mi për shkatërrimin e bijës së popullit tim.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Syri im derdh lot pa pushim, pa ndërprerje,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 deri sa Zoti të mos vështrojë nga qielli dhe të mos shikojë.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Syri im i sjell dhembje shpirtit tim për të gjitha bijat e qytetit tim.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Ata që më urrejnë pa shkak më kanë gjuajtur si të isha zog.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Kanë shkatërruar jetën time në gropë, më kanë hedhur gurë.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Ujrat rrjedhin mbi kokën time, unë thoja: “Ka marrë fund për mua”.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Përmenda emrin tënd, o Zot, nga thellësia e gropës.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ti e dëgjove zërin tim; mos ia fshih veshin tënd psherëtimës sime, thirrjes time për ndihmë.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Kur të kam thirrur ti je afruar; ke thënë: “Mos ki frikë!”
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 O Zot ti ke mbrojtur çështjen e shpirtit tim, ti ke çliruar jetën time.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 O Zot, ti ke parë dëmin që kam pësuar, prandaj mbro çështjen time!
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Ti ke parë tërë frymën e tyre të hakmarrjes, intrigat e tyre kundër meje.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Ti ke dëgjuar fyerjet e tyre, o Zot, tërë intrigat e tyre kundër meje,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 fjalimet e tyre që ngrihen kundër meje, atë që mendojnë kundër meje tërë ditën.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Vër re kur ulen dhe kur ngrihen, unë jam kënga e tyre.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Shpërbleji, o Zot, sipas veprës së duarve të tyre.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Bëji zemërgur, mallkimi yt qoftë mbi ta.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Ndiqi në zemërimin tënd dhe shkatërroi poshtë qiejve të Zotit.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Vajtimet 3 >